Nàìjíríà
orílẹ̀-èdè olómìnira ní Ìwọ̀òrùn Áfríkà / From Wikipedia, the free encyclopedia
Nàìjíríà (pípè /naɪˈdʒɪrɪə/) jẹ́ Orílẹ̀-èdè Olómìnira Ìjọba Àpapọ̀ ilẹ̀ Nàìjíríà (Nigeria ni èdè Gẹ̀ẹ́sì) jẹ́ orílẹ̀-èdè ìjọba àpapọ̀ olómìnira tí ó ní ìjọba ìpínlẹ̀ mẹ́rindínlógójì tó fi mọ́ Agbẹ̀gbẹ̀ Olúìlú Ìjọba Àpapọ̀. Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà wà ní apá Iwọ̀ Oòrùn ilẹ̀ Áfríkà. Orílẹ̀-èdè yí pààlà pẹ̀lú orílẹ̀-èdè Benin ní apá ìwọ̀ Oòrùn, ó tún pààlà pẹ́lú orílẹ̀-èdè olómìnira ti Nijẹr ní apá àríwá, Chad àti Kamẹróòn ní apá ìlà Oòrùn àti Òkun Atlantiki ni apá gúúsù. Abuja ni ó jẹ́ Olú-Ìlú fún orílẹ̀-èdè náà. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Nàìjíríà ní ẹ̀yà púpọ̀, àwọn ẹ̀yà mẹ́ta ni wọ́n hànde tí wọ́n tóbi jùlọ, tí wọ́n sì pọ̀ jùlo, tí a sì kó àwọn ẹ̀ka ìsọ̀rí ìsọ̀rí èyà tókù sí abẹ́ wọn. Àwọn wọ̀nyí ni Ẹ̀ya Hausa, Ẹ̀ya Ìgbò ati Yorùbá.
Ṣíṣàtúnṣe àyọkà yìí látọwọ́ àwọn oníṣe tuntun tàbí àwọn oníṣe aláìtíìforúkọsílẹ̀ jẹ́ tí tìpa lọ́wọ́lọ́wọ́. See the protection policy and protection log for more details. If you cannot edit this àyọkà and you wish to make a change, you can submit an edit request, discuss changes on the talk page, request unprotection, log in, or create an account. |
Orílẹ̀-èdè Olómìnira Ìjọba Àpapọ̀ ilẹ̀ Nàìjíríà | |
---|---|
Motto: "Ìṣọ̀kan àti Ìgbàgbọ́, Àlàáfíà àti Ìlọsíwájú" | |
Olùìlú | Àbújá 9°4′N 7°29′E |
Ìlú tótóbijùlọ | Èkó 6°27′N 3°23′E |
Àwọn èdè ìṣẹ́ọba | Gẹ̀ẹ́sì |
Àwọn èdè ọmọ orílẹ̀-èdè | |
Àwọn èdè míràn[1] | |
Orúkọ aráàlú | Ará Nàìjíríà |
Ìjọba | Orílẹ̀-èdè olómìnira olóòfin-ìbágbépọ̀ ààrẹ ìjọba àpapọ̀ |
• Ààrẹ | Bọ́lá Tinúbú |
Kashim Shettima | |
• Ààrẹ Ilé Alàgbà | Godswill Akpabio |
• Agbẹnusọ Ilé Aṣojú | Tajudeen Abbas |
Olùdájọ́ Olukayode Ariwoola | |
Aṣòfin | Iléìgbìmọ̀ Aṣòfin |
• Ilé Aṣòfin Àgbà | Ilé Alàgbà |
• Ilé Aṣòfin Kéreré | Ilé àwọn Aṣojú |
Òmìnira kúrò lọ́wọ́ Ilẹ̀ọba Aṣọ̀kan | |
• Ìsopọ̀ Apágúúsù àti Apáàríwá Náìjíríà | 1 January 1914 |
• Jẹ́ fífilọ́lẹ̀ àti dídálóhùn | 1 October 1960 |
• Ó di orílẹ̀-èdè olómìnira | 1 October 1963 |
• Òfin-ìbágbépọ̀ lọ́wọ́ | 29 May 1999 |
Ìtóbi | |
• Total | 923,769 km2 (356,669 sq mi) (32nd) |
• Omi (%) | 1.4 |
Alábùgbé | |
• 2020 estimate | 206,630,269[2] (7th) |
• 2006 census | 140,431,691 |
• Ìdìmọ́ra | 218/km2 (564.6/sq mi) (42nd) |
GDP (PPP) | 2020 estimate |
• Total | $1.275 trillion[3] (23rd) |
• Per capita | $6,232 (129th) |
GDP (nominal) | 2020 estimate |
• Total | $504.57 billion[3] (27th) |
• Per capita | $2,465 (137th) |
Gini (2020) | 35.1[4] medium |
HDI (2018) | ▲ 0.534[5] low · 158th |
Owóníná | Naira (₦) (NGN) |
Ibi àkókò | UTC+01:00 (WAT) |
Ojúọ̀nà ọkọ́ | ọ̀tún |
Àmì tẹlifóònù | +234 |
Internet TLD | .ng |
Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ní ìtàn fífẹ̀, bẹ́ẹ̀ sì ni ẹ̀rí ìmọ̀-aíyejọ́un fihàn pé àwọn ìgbé ènìyàn ní agbègbè ibẹ̀ lọ sẹ́yìn dé kéré pátápátá ọdún 9000 kJ.[6] Agbegbe Benue-Cross River jẹ́ rírò gẹ́gẹ́ bí ile àkókó àwọn Bantu arókèrè ti wón fán káàkiri òpó ààrin àti apágúúsù Áfríkà bí irú omi ní ààrin ẹgbẹ̀rúndún akoko àti ẹgbẹ̀rúndún kejì.
Orúkọ Nàìjíríà wá láti Odò Ọya, tí a tún mọ̀ gẹ́gẹ́ bíi Odò Náíjà, èyí tó sàn gba Nàìjíríà kọjá. Flora Shaw, tí yíò jẹ́ ìyàwó lọ́jọ́ wájú fún Baron Lugard ará Britan tó jẹ́ alámójútó àmúsìn, ló sẹ̀dá orúkọ yìí ní òpin ọdún 1897.
Nàìjíríà ni orílẹ̀-èdè tó ní èèyàn púpò jùlọ ní Ilẹ̀ Aláwọ̀dúdú, ikejo ni agbaye[7], bẹ́ẹ̀ sì ni ó jẹ́ orílẹ̀-èdè tó ní àwọn eniyan alawodudu jùlọ láyé. Ó wà lára àwọn orílẹ̀-èdè tí a ń pè ní "Next Eleven" nítorí okòwò wọn, ó sì tún jẹ́ ọ̀kan nínú Ajoni àwọn Ibinibi. Okòwò ilẹ̀ Nàìjíríà jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn èyí tó ń dàgbà kíákíá jùlọ lágbàáyé pẹ̀lú IMF tó ń gbèrò ìdàgbàsókè 9% fún 2008 àti 8.3% fún 2009.[8][9][10][11] Ní ìbẹ̀rẹ̀ àwọn ọdún 2000 sókè, ogunlọ́gọ̀ àwọn ọmọ Nàìjíríà gbé pẹ̀lú iye tó dín ní US$ 1.25 (PPP) lójúmọ́.[12] Nàìjíríà ní okòwò rẹ̀ tóbi jùlọ ní Áfíríkà, ati alágbára ní agbègbè Iwoorun Afirika.